Wo àwọn báǹkì alábọ́de 46 tí CBN gba ìwe àṣẹ wọn àti ìdí tó fi ṣe bẹ́ẹ̀

Oríṣun àwòrán, KC Nwakalor/Bloomberg via Getty Images
Banki apapọ Naijiria, CBN ti kede pe oun ti gbẹsẹle iwe aṣẹ awọn ile ifowopamọ alabọde mẹrindinlaadọta ni Naijiria.
Gẹgẹ bii atẹjade kan ti agbẹnusọ banki ọhun, Hakama Sidi-Ali fi lede, o ni lẹsẹkẹsẹ ni aṣẹ naa yoo bẹrẹ si n mulẹ.
Atẹjade naa sọ pe, "Bẹrẹ lati ọjọ kinni, oṣu Keje, ọdun 2026, banki apapọ Naijiria, CBN ti wọgile iwe aṣẹ iṣẹ awọn ile ifowopamọ mẹrindinlaadọta gẹgẹ bii agbara ti abala kejila ati ikẹtala ofin ile ifowopamọ ti ọdun 2020 fun."
Gomina CBN, Olayemi Cardoso lo buwọlu gbigbẹsẹle iwe aṣẹ awọn ile ifowopamọ naa latari pe wọn kuna lati ni awọn amuyẹ to yẹ gẹgẹ bii ile ifowopamọ.
Eredi ti CBN fi wọgile iwe aṣẹ awọn banki naa
CBN mẹnuba idi marun un ọtọtọ to fi gbe igbesẹ gbibẹsẹle iwe aṣẹ awọn ile ifowopamọ naa.
Akọkọ ni pe awọn ile ifowopamọ ọhun ko ni owo to to ni ipamọ lati san fun awọn onibara wọn to ba kogbawọle.
Ekeji ni pe wọn n pari awọn iṣẹ kan lai kọkọ gba aṣẹ lọwọ CBN.
Ẹkẹta ẹsun ti CBN fi kan wọn ni pe wọn ko ṣiṣẹ bo ṣe tọ ati bo ṣe yẹ.
CBN ni wọn tun kọ lati bẹrẹ iṣẹ laarin oṣu mejila ti wọn gba iwe aṣẹ lati maa ṣiṣe.
Nigba ti ẹsun karun un jẹ kikuna lati ni iye owo to yẹ ni apo wọn lai padanu iye kankan ninu owo ọhun.
Awọn ile ifowopamọ ti ọrọ naa kan ree
- Minji-Se Churchill MFB
- Merchant MFB
- Janmaa MFB
- Busu MFB
- Gold MFB
- Zain MFB
- Bompai MFB
- Ajwa MFB
- NOW NOW Digital MFB
- Crystabel Microfinance Bank
- Chanelle MFB
- Abia SME MFB
- Kamba MFB
- Iwade MFB
- Winview MFB
- ru MFB
- Minjibir MFB
- Shanono MFB
- Sumaila MFB
- Rimin Gado MFB
- Mwaghavul MFB
- camore MFB
- TOFA MFB
- Safegate MFB
- Creekline MFB
- Bestar MFB
- Livingspring MFB
- ple MFB
- Stanford MFB
- Frontline MFB
- Zafec MFB
- Supreme MFB
- Bejin-Doko MFB
- Kanopoly MFB
- Bellbank MFB
- Yeneng MFB
- Creditville MFB
- MBAG MFB
- Sraight Sahara MFB
- OurPass MFB
- Verdant MFB
- Basawa MFB
- Casha MFB
- Esteem MFB
- Entrepreneur MFB
- Avantus MFB
CBN sọ pe afojusun oun ni lati lati ri daju awọn ile ifowopamọ to n ṣiṣẹ ni Naijiria ni awọn amuyẹ to tọ lati ko araalu sinu gbese kankan.


























