BBC News, Yorùbá - Ìròyìn
Ìròyìn tó ṣe kókó
Àwọn agbébọn ṣíná ìbọn bolẹ̀ nígboro South Africa, èèyàn méjìlá kú, mẹ́sàn-án farapa
Gẹgẹ bi akọsilẹ ṣe fi han, orilẹede South Africa wa lara awọn ilu ti wọn ti n pa eeyan ju lagbaaye.
Ẹ̀sùn jìbìtì N69m mí-ìn tún wọlé tọ Blessing CEO, yàtọ̀ sí ti 36m tí wọ́n kọ́kọ́ torí rẹ̀ fi pamọ́ sí àhámọ́
Ọjọ Iṣẹgun, ọjọ kẹsan-an oṣu Kẹfa ni ile ẹjọ giga ipinlẹ Eko fi aaye oniduuro silẹ fun Blessing to ti wa lahamọ EFCC lati oṣu to kọja, pẹlu miliọnu mẹwaa naira, ṣugbọn ahamọ EFCC lo pada si.
Ìsọ̀rí tí orílẹ̀èdè kọ̀ọ̀kan wà ní ìdíje ife ẹ̀yẹ àgbáyé ọdún 2026 àti pápá tí wọn yóò ti gbá bọ́ọ̀lù
BBC ṣe àlàyé lórí ìsọ̀rí tí orílẹ̀èdè kọ̀ọ̀kan wà ní ìdíje ife ẹ̀yẹ àgbáyé tí ọdún 2026 tí yóò bẹ̀rẹ̀ ní ọla Ọjọ́bọ.
Fídíò, "Àwọn agbébọn tó ń jà fún ẹ̀sìn gan ń lo òògùn ìbílẹ̀, ṣé ìjọba le fi 1000 Kùránì àti 1m Bíbélì jagun agbébọn báyìí?", Duration 5,36
Bí ọ̀pọ̀ èèyàn ṣe ń bèèrè pé kí làwọn oníṣẹ̀ṣe fẹ́ ṣe láti dẹ́kun ààbò tó mẹ́hẹ, BBC News Yoruba bá díẹ̀ lára àwọn oníṣẹ̀ṣe sọ̀rọ̀ láti mọ̀ bóyá ètùtù wà tó le ṣẹ́gun ìgbésùnmọ̀mí.
Ìdàrúdàpọ̀ gba ọ̀pọ̀ ìlú ní Osun, èèyàn kan ku, ọ̀pọ̀ farapa bí APC àti Accord ṣe gbéná wojú ara wọn
Awọn agbegbe bii Ile Ife, Owode, Aisu, Olaiya ati Oke-Fia ni rogbodiyan naa tun kan, eyi to mu araalu maa sa asala fun ẹmi wọn.
Kí ni òfin sọ nípa wíwo ilé táwọn ajínigbé bá fi ṣe ibùgbé?
BBC News Yoruba kan si amofin Ademola Owolabi lati ṣalaye ohun ti ofin sọ nipa wiwo ile tawọn ajinigbe ba n lo fi ṣe ibugbe.
MURIC, ẹgbẹ́ Mùsùlùmí nàká àìtọ́ síjọba Oyo pé ó ló ìjínigbé Ogbomoso tako Islam, ìjọba sọ ìdí tí kò ṣe ní fèsì sí ẹ̀sùn náà
Kọmiṣọna fun eto iroyin ni ipinlẹ Oyo, Ọmọba Dotun Oyelade, sọ fun BBC Yoruba wi pe lati ọjọ ti wọn ti ji awọn akẹkọọ ati olukọ lọ ni Esinele ati Yawota l’Ogbomoso ni ijọba ti pinnu pe oun ko ni maa ṣe arohunbọhun pẹlu ẹnikankan lori iṣẹlẹ naa.
Rélùwéè yà kúrò lójú irin, èèyàn mẹ́ta kú
Ileeṣẹ NRC to n ri si ọrọ ọkọ ofurufu ni Naijiria, ṣalaye pe ẹka mẹrin lo ya kuro lara ọkọ oju irin naa.
Orin, Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́, Duration 1,00
Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Èèyàn mẹ́rin míràn ni ajínigbé tún pa ní Mowe, kì í ṣe ṣọ́jà nìkan - Iléeṣẹ́ ológun
Ninu atẹjade ti Ọgagun Idereghi Samuel Akari, Igbakeji ọga to n ri si ikede nileeṣẹ ologun 35 Artillery Brigade, Alamala niluu Abeokuta, fi sita lo ti ṣalaye eyi.
Àṣírí abilékọ̀ tó jí ara rẹ̀ gbé, béèrè ₦50m owó ìtúsílẹ̀ tú, ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ nílé ìtura
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Edo, Eno Ikoedem, ni lọjọ kinni oṣu Kẹfa yii ni ọkunrin kan niluu Benin fi to ọlọpaa pe wọn ti ji iyawo oun, Oluchi Ugbowan ẹni ọdun marundinlaadọta gbe lọ.
BBC News Yorùbá ti wà lórí ìkànnì WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ
Ìròyìn Àkàgbádùn
Mò sunkún lórí àwọn ọmọ tí wọ́n jí gbé l'Ogbomoso, mi ò mọ̀ pé tèmi náà yóò ṣẹlẹ̀ sí mi - Iya Adelabu
Kọmisona ọlọpaa Oyo ṣàlàyé pe awọn oṣiṣẹ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ ti ijọba apapọ, pẹlu àjọṣepo awọn oṣiṣẹ ile iṣẹ ọlọ́pàá nipinlẹ Oyo lọ pawọpọ sisẹ idoola ẹ̀mí náà.
Ṣé lóòótọ́ ni pé Sunday Igboho ló ṣe bí wọ́n ṣe gba ìtúsílẹ̀ àbúrò Adelabu àtàwọn ọmọ rẹ̀? Ohun tí a mọ̀ rèé
Alẹ ọjọ Satide, ọjọ kẹfa oṣu Kẹfa ọdun 2026 yii ni ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria fidi eyi mulẹ, ninu atẹjade ti Alukoro apapọ; DCP Anthony Okon Placid, fi sita l'Abuja.
Ẹ lo agbára àwọn alálẹ̀ láti ṣẹ́gun ìgbéṣùmọ̀mí - Ooni
Ninu alaye rẹ, Ooni Ogunwusi sọ pe o di dandan fun awọn ọba alaye kaakiri ilẹ Yoruba lati mu agbara iṣẹdalẹ lo.
'Ẹ̀sìn àbáláyé ló le yọ Nàìjíríà kúrò nínú ìpèníjà ààbò'
Bi awọn araalu ṣe n wa ojutuu si ipenija aabo Naijiria ni awọn ori ade ọrun ilẹkẹ ko dakẹ, ti wọn n fi imọran lede lori ọna ti wọn ro pe o le mu aabo pada silu.
Ikọ̀ ọmọ ogun Isreali ṣekúpa olórí Hamas, Abu Karim
Ọjọ Aiku, ọjọ keje oṣu Kẹfa ọdun 2026 ni ikọ ologun Israeli sọ eyi di mimọ loju opo X wọn ti wọn ti kede.
Ṣé lóòótọ́ ni Boko Haram yọ̀ǹda èèyàn 416 tí wọ́n jí gbé ní Borno? Ohun tí a mọ̀ rèé
Ọpọ obinrin ati awọn ọmọde ni wọn pe awọn ti wọn ni Boko Haram tu silẹ naa.
Nàìjíríà kéde èròńgbà láti kó àwọn èèyàn rẹ̀ ní South Africa padà sílé bí ìwọ́de tako àwọn àjòjì ṣe tún peléke síi
Igbesẹ yii lo n waye bi iwọde tako awọn ajoji ṣe n peleke si ni South Africa, tawọn orilẹ ede si n kọminu lori awọn eeyan wọn to wa ni South Africa.
Oriyomi Hamzat ṣàlàyé àjọsẹpọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú Sheikh Gumi, ìgbésùnmọ̀mí àti akatakítí ẹ̀sìn
Ni itẹsiwaju alaye rẹ, Oriyomi Hamzat sọ pe oun ko ṣalaye ọrọ yii nitori ki araalu le dibo foun rara.
Àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú jànkàn tó lè má kópa nínú ètò ìdìbò ọdún 2027
Eyii ko ṣẹyin awọn oniruru ipẹjọ to n waye lẹyin alakalẹ INEC naa.
Ṣé lóòótọ́ ni ọmọbìnrin akẹ́kọ̀ọ́ kan ti kú sígbèkùn ajínigbé nínú àwọn tí wọ́n jí gbé l'Ogbomoso? Àlàyé rèé
Iroyin naa lo tubọ mu ibanujẹ ati ikayasoke wa, bẹẹ ni o da omi tutu si ọkan ọpọ ọmọ Naijiria.
Èyí lohun tí òfin sọ nípa àwọn tó bá ń gbé ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀ pé jàndùkú wọ ìlú àti ìjìyà tó wà fún un
Awọn ipinlẹ ti awọn eeyan ti gbe iroyin ẹlẹjẹ pe agbesunmọmi wọ ilu ati ohun ti ofin sọ nipa pinpin iroyin ẹlẹjẹ.
Ìgbákejì alága ìjọba ìbílẹ̀ l'Ekiti tí ọlọ́pàá ló jí ara rẹ̀ gbé dèrò àtìmọ́lé
Ogunjọ osu karun ọdun 2026 niroyin kan jade wi pe wọn ti ji arabinrin Ogunleye, igbakeji alaga ijọba ibilẹ ilejemeje gbe lọ nipinlẹ Ekiti.
Ìròyìn Pàtàkì
Kọ́milẹ́kọ̀ọ́
Ẹ tẹ̀lé wa lórí ìkànnì ayélujára
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Yinka Alaseyori ṣàlàyé ara rẹ̀ lórí fídíò tó ṣe nípa àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àtàwọn olùkọ́ tí wọ́n jí gbé l'Ogbomoso
Ṣaaju ni Yinka ti sọ ninu fidio kan to gbe jade wi pe kawọn ọmọ Naijiria tẹsiwaju lati maa gbadura lori eto aabo to mẹhẹ.
Ilé ẹjọ́ dájọ́ ikú fún mẹ́rin nínú afurasí márùn ún fún ìkọlù ìjọ Kátólíkì nílùú Owo, tí wọ́n ti pa èèyàn 41 lọ́dún 2022
Ikọlu naa to waye ni ọjọ karun un oṣu kẹfa ọdun 2022 ninu eyi ti olujọsin mọkanlelogoji ti jade laye ti ogoje miran si farapa.
Ta ni Kingsley Chinda tó kúrò ní ẹgbẹ́ òṣèlú PDP lọ sí APC láti du ipò gómìnà ní ìpínlẹ̀ Rivers?
Ninu lẹta kan ti Kingsley Chinda kọ sile ọhun lọjọ kẹtalelogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2026 yii amọ ti wọn ka ninu ile ọhun lana ọjọ keji, oṣu Kẹfa, ọdun 2026 lo ti fidi ọrọ naa lede.
Mo kọ N500m tí wọ́n fi lọ̀ mi láti dènà Ajimobi nígbà tó fẹ́ di gómìnà, àmọ́ ó padà gbàgbé mi- Taiwo Otegbeye
Taiwo Otegbeye lo dupo gomina ninu ẹgbẹ oṣelu Action Alliance, ni 2011.
Àwọn ilé ẹ̀kọ́ tilẹ̀kùn wọn pa l'Osun nítorí ìròyìn pé agbébọn wọ ìlú, Adeleke ní kò sí ohun tó jọ bẹ́ẹ̀
Adeleke ni awọn ọta ilu atawọn ọmọ ẹgbẹ alatako lo n gbe iroyin ẹlẹjẹ naa iri.
Ìjàmbá ọkọ̀ ló fa ikú òṣèré tíátà, 'Janmole' - Mr Latin
Aarẹ ẹgbẹ awọn oṣere TAMPAN, Ọgbẹni Bolaji Amusan, tawọn eeyan mọ si Mr Latin lo fi iroyin iku naa lede loju opo Instagram rẹ.
Èyí làwọn olóṣèlú tó fẹ́ dupò ààrẹ ní 2027 tórúkọ wọn gbilẹ̀ jù
Awọn ẹgbẹ alatako torukọ wọn gbilẹ ju ni ADC, NDC ati PDP
Àwọn orílẹ̀èdè Áfríkà wo ló jẹ àjọ IMF lówó jùlọ ?
Bi o tilẹ jẹ pe awọn orilẹede maa n lo owooya lati ajọ IMF lati fi ṣe eto ọrọ aje wọn, ẹru wiwo gbese ọlọjọ gbọọrọ lee bẹgidina idagbasoke.
Kókó ohun tó jẹyọ lásìkò àbẹ̀wò ìgbìmọ ìjọba àpapọ̀ sí Ogbomoso lórí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àtàwọn olùkọ́ tí wọ́n jí gbé
Igbimọ naa kọminu lori iṣẹlẹ ọhun, wọn si ṣeleri pe Aarẹ Bola Tinubu yoo sa gbogbo agbara rẹ lati doola gbogbo awọn ti wọn ji gbe.











































































