Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Ijọba apapọ ti fesi si awọn ọmọ orilẹede Ghana ti wọn ni ki awọn ọmọ Naijiria pada sorilẹede wọn latari iwa laabi ti wọn n wu nibẹ
Ajọ to n ri si ọrọ awọn ọmọ Naijiria nilẹ okere, NIDCOM sọ pe, awọn ọmọ Naijiria kii ṣe ọdaran bi wọn ṣe sọ, ati pe ọmọ iya kan naa ni Ghana ati Naijiria
_________________________
Lọ soju opo BBC Yoruba fun ẹkunrẹrẹ
Ẹgbẹ awọn nọọsi lawọn ile iwosan ijọba apapọ kaakiri Naijiria ti bẹrẹ iyanṣẹlodi laarọ oni Ọjọru
Eredi iyanṣẹlodi ọhun ko ṣẹyin ọwọ ti ijọba fi mu owo oṣu atawọn ajẹmọnu mii to tọ si wọn
Ẹwẹ, ẹgbẹ awọn dokita, NMA naa ti sọ pe awọn yoo bẹrẹ iyanṣẹlodi tiwọn laipẹ
_________________________
Ni Ivory Coast
Aarẹ Alassane Ouattara ti kede pe oun yoo dije du ipo fun saa kẹrin
Ẹni ọdun mẹtalelọgọrin naa ni ilera oun ti ko duro dede ko le ṣakoba kankan fun ijọba oun
Ọdun 2011 ni Ouattara gba ọpa aṣẹ Ivory Coast lẹyin ogun abẹle to waye nibẹ
Fun ẹkunrẹrẹ